Ní Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yoruba, D.R.Y), gẹ́gẹ́bí Ìyá wa Ìyá-Ààfin Modúpẹ́ Onítirí-Abíọ́lá ṣe sọ, ìwòsàn ọ̀fẹ́ wà fún ojúlówó Ọmọ-Ìbílẹ̀ Yorùbá (Indigenous Yorùbá People, I.Y.P), lóòrè-kóòrè.

Àrùn-ọpọlọ èyí tí ó nmú ènìyàn ṣe àrìn-kiri ojú pópó ni D.R.Y kò ní gbà láàyè. Àkọ́kọ́, ọmọ aládé kò ní máa rìn-gboro kiri láì ní ìtọ́jú.

Èkéjì, orílẹ̀-èdè wa ní ètò tí ó yanran-ntí láti rí pé àjòjì tó bá wá sí ilẹ̀ D.R.Y kò ní jẹ́ alárín kiri tàbí ẹni tó máa di bùkátà s’ọ́rùn D.R.Y.

Nínú ohun gbogbo, ẹ jẹ́ kí á rántí pé Indigenous Yorùbá People (I.Y.P) ni ẹyin-lójú orílẹ̀-èdè wa.

Bí a ṣe máà mọ I.Y.P, ìyẹn wà ní ọgbọ́n, ìmọ̀ àti òye tí Olódùmarè yọ̀nda fún D.R.Y, pàápàá ní títẹ̀lé Àlàkalẹ̀ tí Ó gbé fún wa, nípasẹ̀ Màmá wa, Ìyá-Ààfin Modúpẹ́ Onítirí-Abíọ́lá.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.